Awọn ajinigbe pa alaga Miyetti Allah lẹyin ti wọn gbowo tan  

Faith Adebọla

  Alaga ẹgbẹ awọn darandaran onimaaluu, Miyetti Allah Cattle Breeders Association of Nigeria (MACBAN), Alaaji Abubakar Abdullahi, ti inagijẹ rẹ n jẹ Danbardi, tawọn janduku agbebọn ji gbe l’Ọjọbọ, Tọsidee, ọsẹ yii, ti dagbere faye lẹyin ọjọ keji lakata awọn ti wọn ji i gbe.

Atẹjade latọwọ Ọgbẹni Othman Ngelzarma, Akọwe apapọ ẹgbẹ MACBAN, ṣalaye lọjọ Abamẹta, Satide, yii pe iku Abubakar yii lo sọ ọ di ẹni karun-un tawọn janduku agbebọn, awọn ajinigbe atawọn to n jale maaluu yoo pa nipa ika lẹnu ọjọ mẹta yii lara awọn ọmọ ẹgbẹ awọn, bẹẹ awọn mọ pe ọpọ ọmọ ẹgbẹ naa lawọn ika ẹda yii n pa ti ko si akọsilẹ fun wọn.

“Alaaji Abubakar, ẹni ọdun mejidinlọgọta, to jẹ alaga ẹgbẹ MACBAN nijọba ibilẹ Lere, nipinlẹ Kaduna, lawọn ajinigbe ji gbe lọjọ kẹrindinlogun, oṣu kẹsan-an, lẹyin tawọn mọlẹbi ẹ si ti san owo ti wọn beere fun itusilẹ rẹ lo jẹ oku rẹ ni wọn ba lẹgbẹẹ titi laṣaalẹ ọjọ keji, ọjọ Ẹti, Furaidee, ọjọ kẹtadinlogun, oṣu kẹsan-an, lọna to wọ ilu Lere.

‘‘A daro gidigidi pẹlu awọn mọlẹbi oloogbe yii, a si fi ẹdun ọkan wa han pẹlu awọn ọmọ ẹgbẹ ati alakooso ẹgbẹ MACBAN, a ṣadura ki Allah rọ wọn lọkan lori iṣẹlẹ ibanujẹ yii.

A n fi asiko yii ke si awọn agbofinro lati wadii iku ojiji yii ki wọn si fiya to tọ jẹ awọn ti wọn lọwọ ninu iwa odoro naa.

A fẹẹ ṣekilọ pe ti iwa ọdaran bii eyi ba n ba a lọ, o maa mu ko tubọ ṣoro fawọn darandaran lati ṣe ọrọ-aje wọn lorileede yii, eyi si maa mu ki ẹran wọn gogo gan-an.

A fẹ kijọba apapọ ṣeto ofin to maa daabo bo awọn darandaran kaakiri orileede yii, ki wọn le maa ṣọrọ-aje wọn lai si ifoya.

Leave a Reply