Awọn agbebọn tun ji akẹkọọ ọgọrun-un meji gbe nileewe kan ni Niger

Awọn ajinigbe tun ya wọn ileewe kan ti wọn pe ni Islamiyya School, to wa ni Tegina, nijọba ibilẹ Rafi, nipinlẹ Niger, wọn si ko awọn akẹkọọ ọgọrun-un meji lọ.

Ni nnkan bii aago mẹrin aabọ ọjọ Aiku, Sannde, ọsẹ yii la gbọ pe wọn ya bo ileewe naa, ti wọn si bẹrẹ si i yinbọn. Ibọn yii ba ẹni kan, nigba ti ẹlomi-in to fara kaasa ibọn yii wa lọsibitu to ti n gbatọju nitori ibọn naa ba a gidigidi.

ALAROYE gbọ pe ileewe ti wọn ti n kọ awọn ọmọ ni keu ni ileewe naa, awọn obi kọọkan lo si maa n mu awọn ọmọ wọn wa sibẹ lati waa kẹkọọ.

Bo tilẹ jẹ pe Akọwe ijọba nipinlẹ Niger, Ahmed Matane, ni awọn ko ti i mọ iye awọn akẹkọọ ti wọn ko lọ, sibẹ, awọn olugbe agbegbe tiṣẹlẹ yii ti ṣẹlẹ sọ pe awọn akẹkọọ ti wọn ko to ọgọrun-un meji.

Yatọ si agbegbe Tegina tawọn agbebọ naa ti ṣọṣẹ, a gbọ pe wọn tun ṣoro ni awọn ijọba ibilẹ meji mi-in, eyi to mu ko nira fawọn agbofinro lati mọ eyi ti wọn fẹẹ koju ninu wọn.

Leave a Reply