Awọn alaṣẹ ti jawee ‘gbele ẹ’ fun Biṣọọbu Adepọju l’Ekiti, wọn lo n ba’yawo alufaa to wa labẹ ẹ sun

Dada Ajikanje

Ohun ti ọkan ninu awọn oluṣọagutan ijọ Anglican, The Retd Revd Biṣọọbu Ajilẹyẹ Adepọju, ko ro lo ba pade pẹlu bi awọn adari ijọ naa ṣe jawee gbele-ẹ fun un nitori ẹsun agbere ti wọn fi ka an.

Biṣọọbu yii ni adari gbogbo ijọ naa ni Iwọ Oorun Ekiti, ẹsun ti wọn si fi kan an ni pe o n ba iyawo ọkan ninu awọn alufaa to wa labẹ rẹ lo pọ. Ọkunrin naa si ti jẹwọ nigba ti wọn pe e siwaju awọn igbimọ oluwadii kan lọjọ kẹwaa, oṣu kejila yii, pe loootọ loun huwa buruku naa.

 

Ninu iwe ti wọn kọ si ọkunrin naa lati da a duro fungba diẹ, eyi ti Oluṣọagutan Henry C. Ndukaba fọwọ si lo ti kọ pe ‘‘ Pẹlu ọkan wuwo la fi kọwe ‘gbele ẹ’ fun ọ gẹgẹ bii Biṣọọbu Diocesan Anglican Ekiti West.

‘‘Igbesẹ yii ko sẹyin iwa idojutini ti o hu pẹlu bi o ṣe n ba ọkan ninu awọn iyawo alufaa to wa labẹ rẹ ni ajọṣepọ, to o si fidi ọrọ yii mulẹ ninu ipade ti a ṣe pẹlu rẹ ni ọọfiisi wa ni Ọjọbọ, Tọsidee, ọjọ kẹwaa, oṣu kejila yii.

‘‘Pẹlu igbesẹ yii, o ko gbọdọ kopa ninu ohunkohun gẹgẹ bii biṣọọbu agbegbe naa fun odidi ọdun kan gbako latọjọ ti o ba ti gba iwe yii.

‘‘Ki o si yọju si biṣọọbu agba fun itọni ti ẹmi siwaju si i.’’

Leave a Reply