Baba agbalagba to n ba ọmọ ọdun mẹwaa lo pọ n’Ilọrin ni oun lo gba foun

Stephen Ajagbe, Ilorin

Ọwọ ṣinkun ajọ aabo ẹni laabo ilu, NSCDC, tipinlẹ Kwara, ti tẹ baba ẹni ọdun marunlelọgọta kan, Samuel Darisa, ti wọn fẹsun kan pe o n ba ọmọ ọdun mẹwaa laṣepọ lagbegbe Agbadam, niluu Ilọrin.

Nigba ti wọn ṣafihan rẹ lọjọ Ẹti, Furaidee, ọsẹ yii, ni olu ileeṣẹ NSCDC, afurasi naa ni ki i ṣe pe oun fipa ba ọmọ naa sun o, o loun lo maa n gba foun lati ba a laṣepọ, ati pe ki i ṣe ẹẹkan tabi ẹẹmeji tawọn ti n ṣe e.

Ọga ajọ NSCDC nipinlẹ Kwara ni ọkan lara awọn ayalegbe ti wọn jọ n gbele lo ri wọn lasiko ti wọn n ba ara wọn sun, to si ta araadugbo lolobo ko too di pe wọn fi pampẹ ọba gbe afurasi naa.

Alukoro ileeṣẹ naa, Babawale Zaid Afọlabi, ni iwadii ṣi n tẹsiwaju, o ni laipẹ lawọn yoo wọ ọ lọ sile-ẹjọ.

Leave a Reply