Gbajabiamila ṣabẹwo si Sanwo-Olu, Akiolu ati Tinubu, o ṣeleri iranlọwọ

Faith Adebọla

Olori ileegbimọ aṣoju-ṣofin niluu Abuja, Fẹmi Gbajabiamila, ti ṣabẹwo si Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu, latari rogbodiyan to ṣẹlẹ nipinlẹ naa, nibi ti ọpọ dukia ijọba ti jona guruguru.

O fi aidunnu rẹ han si iṣẹlẹ naa, bẹẹ lo si ba gomina atawọn eeyan ipinlẹ Eko kẹdun.

Sanwo-olu mu olori awọn aṣoju-sofin to wa l’Abuja naa kaakiri awọn dukia ijọba ti wọn bajẹ.

Bakan naa ni ọkunrin yii ṣabẹwo ibanukẹdun si Ọba ilu Eko, Rilwan Akiolu, lati ba a kẹdun bi wọn ṣe ba afin rẹ jẹ lasiko rogbodiyan to waye lẹyin tawọn ṣọja loọ yinbọn fun awọn ọdọ kan to kora jọ pọ sibi ti wọn ti n ṣe iwọde ni Lẹkki.

Bẹẹ lo fẹsẹ kan de ọdọ Asiwaju Tinubu naa.

Lasiko abẹwo yii lo ṣeleri iranlọwọ awọn aṣofin fun ipinlẹ Eko. O ni awọn yoo nawọ iranlọwọ si wọn ati awọn ipinlẹ mi-in ti wahala yii ti ṣẹlẹ ti awọn ba ti wọle ijokoo pada.

Leave a Reply