‘Ko sohun ti APC ko fi ni i wọle ibo 2023, gbogbo aye lo ri i pe iṣejọba Buhari peregede’

Faith Adebọla

Gomina ipinlẹ Imo, Ọgbẹni Hope Uzodinma, ti ni bi eto idibo gbogbogboo to maa waye lọdun 2023 nilẹ wa ko ba lọwọ kan eru ninu, oun o ri idi ti ẹgbẹ oṣelu APC (All Progressive Congress) ko fi ni i jawe olubori, tori akiyesi toun ṣe ni pe awọn eeyan nifẹẹ bi Aarẹ Muhammadu Buhari ṣe n ṣejọba yii, wọn n gboṣuba gidi fun un ni.

Nigba to n ba awọn oniroyin sọrọ nileejọba ipinlẹ Imo, l’Owerri, lo sọrọ naa lỌjọruu, Wẹsidee.

O ni ojoojumọ ni iye awọn to n di ọmọ ẹgbẹ APC kaakiri orileede wa tubọ n pọ si i, ọgọọrọ awọn eeyan lo si ti ṣetan lati tun dara pọ.

“Ki lo n ṣẹlẹ tabi to fẹẹ ṣẹlẹ ti ko ni i jẹ ki ẹgbẹ APC yege? Ṣe ẹ fẹẹ lẹ o mọ pe ipinlẹ mejilelogun ni APC n ṣakoso rẹ lọwọlọwọ yii ni?

Ẹ jẹ ki n soootọ fun yin, ero tawọn eeyan ni nipa iṣejọba Buhari ni pe Aarẹ n ṣe daadaa gidi, ta a ba yọwọ wahala eto aabo to ti d’ogun kaakiri aye, ati ajakalẹ arun COVID-19 to n ja bii iji kiri gbogbo ilu kari aye, sibẹ, Buhari ko Naijiria yọ lọwọ ojojo to n ṣe ọrọ-aje wa.

Tori naa, ọkan mi balẹ. Inu mi dun pe ọmọ ẹgbẹ APC ni mi, mo si ro pe a maa sa gbogbo ipa wa lati jẹ kawọn eeyan tubọ nigbẹkẹle ẹgbẹ wa, a o si ni i ja wọn kulẹ.”

Bẹẹ ni Uzodinma sọ.

Leave a Reply