Nitori ti wọn ko gba a laye lati kawe, Ọmọyẹle Ṣoworẹ kọ ounjẹ silẹ latimọle

Jide Alabi

Nítorí tawọn ọlọpaa ko jẹ ki ọkunrin akọroyin to nileeṣẹ iroyin Sahara Reporter, Ọmọyẹle Ṣowore, lanfaani sí ìwé tawọn mọlẹbi ẹ ko wa fun un, ọkunrin naa ti ni ebi loun yóò máa fi pa ara oun bayii.
ALAROYE gbọ pe bi awọn eeyan ẹ ṣe ko awọn ìwé ẹ wa, ṣugbọn ti awọn ọlọpaa kọ láti ko o fun un lo fa a ti Ṣowore fi yari pé oun ko ni i jẹ ounjẹ ti wọn ba gbe fún òun, nitori oun ko le máa jẹun sikun, ki oun ma fún ọpọlọ oun lounjẹ.
Aja-fẹtọọ-ọmọniyan yii sọ pe bi oun ba ṣe n jẹun, bẹẹ gẹgẹ loun máa n fún ọpọlọ oun lounjẹ, ati pe awọn iwe ti oun máa n ka ni ounjẹ ti ọpọlọ oun máa n jẹ.
Ni bayii, ọkunrin oniroyin, to tun jẹ oloṣelu yii, ti sọ pe oun yóò bẹrẹ ifẹhonu han, oun yóò sì bẹrẹ sí i febi nla pa ara oun.
Bi Ṣowore ṣe bẹrẹ ifẹhonu hàn yii lawọn ti wọn jọ mu naa ti darapọ mọ ọn, ti gbogbo wọn sì ti lawọn ko ni i jẹun rara.
Laipẹ yii lawọn ẹṣọ agbofinro ko Ṣoworẹ atawọn eeyan ẹ nibi ti wọn ti n ṣewode lati wọnu ọdun tuntun.
Ṣaaju àsìkò yìí, ìyẹn lọjọ kẹta, oṣu kẹjọ, ọdún, 2019, làwọn ẹṣọ agbofinro DSS mu Ṣoworẹ, ti wọn si fi í sí atimọle wọn fún ọjọ mẹrinlelogoje (144).
Ẹsun tí wọn fi kan an ni pe oun naa n kowo pamọ́ lọna eru, ati pe o n gbero lati gbajọba mọ Ààrẹ Muhammadu Buhari, lọwọ.
Pẹlu ẹsun yii, ALAROYE gbọ pe awọn ẹṣọ agbofinro ko ri ẹri kan ko kalẹ lati fi ba a fa a.
Ninu wahala ọhun náà ni wọn ti gbe e lọ sile-ẹjọ, ṣugbọn ti wọn pada fún un ni beeli logunjọ, oṣu kọkanla, ọdun 2020, ti wọn sì pa a laṣẹ pé kò gbọdọ kúrò nílùú Abuja.

Leave a Reply