Wọn yinbọn lu Baba Adinni lasiko tawọn eleegun lọọ da mọṣalaaṣi kan ru l’Oṣogbo

Florence Babaṣọla

Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ọṣun sọ pe awọn ti bẹrẹ iwadii lori wahala kan to bẹ silẹ laarin awọn ẹlẹsin Musulumi atawọn eleegun niluu Oṣogbo lọsan-an ọjọ Aiku, Sannde, ọsẹ yii.

Adura nipa wahala eto aabo orileede Naijiria la gbọ pe awọn Musulumi ọhun n ṣe lọwọ lagbegbe Oluọdẹ Aranyin, n’Ita-Olookan, niluu Oṣogbo, ti wahala naa fi bẹrẹ.

Lojiji lawọn eleegun naa yọ sibẹ, ti wọn si n ju okuta lu awọn ti wọn n ṣadura, ki oloju too ṣẹ ẹ, ọrọ naa ti dariwo.

Bi awọn agbaagba mọṣalaaṣi atawọn ọdọ ṣe n beere ohun tawọn eleegun naa ri lọbẹ ti wọn fi waro ọwọ, iro ibọn ni wọn gbọ lojiji.

Ki wọn too mọ nnkan to n ṣẹlẹ, ibọn ti ba Baba Adinni mọṣalaasi naa torukọ rẹ n jẹ Moshood Salawudeen, loju-ẹsẹ ni baba naa jade laye.

Imaamu mọṣalaaṣi ọhun, Qusum Yunus, fidi iṣẹlẹ naa mulẹ, o ni aago meji aabọ ọsan ọjọ Aiku, Sannde, lo ṣẹlẹ, ati pe adura pe ki Ọlọrun fopin si wahala eto aabo orileede Naijiria lawọn n ṣe lọwọ nigba tiṣẹlẹ naa ṣẹlẹ.

Alukooro ileeṣẹ ọlọpaa l’Ọṣun, Yẹmisi Ọpalọla, ṣalaye pe awọn ti gbọ nipa iṣẹlẹ naa ati pe awọn ti bẹrẹ iwadii lori rẹ.

Leave a Reply