Ibrahim Alagunmu
L’Ọjọ Iṣẹgun, Tusidee, ọsẹ yii, nijọba ipinlẹ Kwara, labẹ iṣejọba Gomina AbdulRahman AbdulRazaq, fẹsun kan ẹgbẹ oṣelu alatako PDP, pe wọn ti bẹrẹ si i ba ijọba to n bẹ lode lorukọjẹ ki wọn le pada sipo lọdun 2023.
Nigba ti olubanidamọran pataki si gomina lori ọrọ oṣelu nipinlẹ Kwara, n ba awọn oniroyin sọrọ niluu Ilọrin, lọjọ Iṣẹgun, o ni afẹfẹ ti fẹ, a ti ri fufọ adiẹ, gbogbo igbesẹ ibanilorukọjẹ ti awọn ẹgbẹ alatako n gbe nipa irọ pipa, ṣiṣe ayederu fidio, iroyin ofege, lati fi ṣi awọn araalu lọna ki wọn le pada sipo ni ọdun 2023, nijọba ti mọ nipa rẹ, ti wọn si fẹẹ maa lo ori ayelujara lati fi gbogun ti ijọba.
O tẹsiwaju pe lara igbesẹ wọn ni eyi ti wọn sọ pe ẹgbẹrun lọna ọọdunrun miliọnu to jẹ owo ijọba ibilẹ poora ninu iṣejọba Gomina AbdulRazaq, to si jẹ pe iwadii fihan pe irọ funfun balau ni. O rọ awọn araalu ki wọn ma gbọ ti ẹlẹgan, ki wọn jinna si awọn iroyin ofege tawọn ẹgbẹ oselu PDP gbe kiri.