Adewale Adeoye
Gbogbo awọn ti wọn ri fidio kan ti Alaaji Kollington Ayinla, ti gbogbo eeyan mọ si Kebe-n-Kwara gbe jade, ni wọn n ba a dupẹ lọwọ Ọlọrun pe baba naa ti wa lalafia, ati pe aisan to ṣe e naa ko mu ẹmi rẹ lọ.
Yin-ni yin-ni kẹni ṣe mi-in ni ọga awọn onifuji ọhun fọrọ naa ṣe pẹlu bo ṣe n dupẹ, to ṣi n fi ẹmi imoore rẹ han si gbogbo awọn ọmọ orile-ede yii nile–loko ati lẹyin odi, paapaa ju lọ, Gomina ipinle Eko, Ọgbẹni Babjide Sanwo–Olu, ọga agba ileewosan ẹkọṣẹ iṣegun tijọba Eko, ‘Lagos State University Teaching Hospital’( LASUTH), Dokita Adetokunbọ Fabanwo, fun itọju pataki to ri gba, ati bi wọn ṣe sa gbogbo ipa wọn lori rẹ, ti aisan buruku to kọ lu u naa ko ran an sọrun ọsan gangan.
Ninu fidio oniṣẹju diẹ kan to ṣe sita lati fi dupẹ lọwọ gbogbo awọn eeyan jankan-jankan to duro ti i lasiko aisan to da a gbalẹ ọhun Kollington ti gbe oṣuba nla fun Ọlọrun Ọba ọga ogo lori bo ṣe ran awọn ẹlẹyinju aanu gbogbo si i lasiko to fi ṣaisan laipẹ yii.
O ni, ‘Ọlọrun Ọba naa ni ma a fi ọpẹ ati iyin fun, nitori pe Ọlọrun Ọba yii ni ọga ogo to ga ju lọ. Lẹyin naa ni ma a dupẹ lọwọ Gomina ipinlẹ Eko, Ọgbẹni Babajide Sanwo–Olu, fun bo ṣe dide iranlọwọ si mi. Bakan naa ni mo tun dupẹ lọwọ ọga agba ileewosan LASUTH, bi gbogbo wọn ṣe n sare sọtun-un sosi lori mi. Mi o tun ni i gbagbe ipa pataki tawọn araalu Eko ko lori mi lasiko ti mo fi wa lori idubule aisan, Ọlọrun Ọba lo le san gbogbo yin lẹsan gidi, lagbara Ọlọrun, a ko ni i firu rẹ san an funra wa o.
Tẹ o ba gbagbe, aipẹ yii ni ariwo gba ilu kan pe ara ọga awọn olorin Fuji naa ko ya. Wọn ni aisan naa le debii pe ẹrọ to n ran eeyan lọwọ lati mi ni wọn so mọ ọkunrin naa nimu to fi n mi, tawọn dokita si ti sọ pe bakan meji ni aisan to n ṣe ọkunrin ọmọ bibi ipinlẹ Kwara ọhun. Ṣugbọn pẹlu iranlọwọ Ọlọrun atawọn dokita ileewosan ijọba naa, Alaaji Kollington ti n ta ‘kebe’ pada bayii bii orukọ rẹ. Beeyan ba si ri i lorii bẹẹdi ọsibitu naa to ti ṣe fido ọhun, tọhun ko le mọ pe baba tawọn dokita n sọ pe awọn ko ti i mọ ibi ti ọrọ rẹ maa ja si ni bii ọjọ meloo kan sẹyin niyẹn.