Sunday Igboho tun juko ọrọ: Ẹru Fulani ni Tinubu, Makinde atawọn agbaagba Yoruba kan

Lẹẹkan si i, Oloye Sunday Adeyẹmọ, ọkunrin ajafẹtọọ iran Yoruba nni ti ṣapejuwe Aṣiwaju Bọla Tinubu, Gomina Ṣeyi Makinde atawọn eeyan kan ti awọn Yoruba n pe ni aṣaaju wọn gẹgẹ bii ẹru Fulani ti wọn ti kuna lati duro ti awọn eeyan wọn ninu wahala ti wọn n la kọja.

Eyi wa lara awọn koko ọrọ pataki to sọ lasiko ipade ti akikanju ọmọ Yoruba yii ṣe pẹlu awọn ọmọ Yoruba ti wọn n gbe lawọn ilẹ okeere kaakiri agbaye lori ẹrọ ayelujara.

O ni bo tilẹ jẹ pe ko si kinni kan bayii to le di gomina yii ati Aṣiwaju Bọla Tinubu lọwọ lati ri Aarẹ Muhammadu Buhari, sibẹ, niṣe ni wọn n ba ojuṣaaju kiri, ti iya buruku si n jẹ awọn eeyan wọn nilẹ Yoruba.

Oloye Sunday Adeyẹmọ sọ pe, “Pupọ ninu awọn aṣaaju ta a ni nilẹ Yoruba ni wọn n sa kiri, ti wọn ko sọ ootọ ọrọ fun Aarẹ Buhari nipa wahala tawọn Fulani n da silẹ nilẹ Yoruba nitori ipo ti wọn n wa nidii oṣelu.”

Igboho fi kun un pe pupọ ninu awọn oloṣelu ilẹ Yoruba ni wọn maa n sọ nnkan mi-in ti wọn ba ti de ilu Abuja, ati pe asiko ti a wa yii, oun ṣetan lati koju ẹnikẹni to ba kẹyin si iran Yoruba lori wahala tawọn janduku Fulani n ko n ko ba awọn eeyan oun.

Ṣiwaju si i, Igboho ni, “O ṣe ni laaanu pe awọn oloṣẹlu ta a ni yii ko ni anfaani kankan ti wọn fẹẹ ṣe fun iran Yoruba, awọn Bọla Tinubu atawọn eeyan ẹ ti di ẹru Fulani, ko si anfaani kan bayii ti wọn le ṣe fun iran Yoruba, awa ni ki a ja funra wa. Ẹyin naa ẹ wo Ṣeyi Makinde ta a dibo fun, ta a ro pe yoo ṣe daadaa, bi yoo ṣe pada wa lẹẹkan si i lo n ba kiri, ti iya buruku si n jẹ iran Yoruba lọwọ Fulani. Eti Ṣeyi Makinde ti di patapata si ariwo ti awọn eeyan ẹ n pa, asiko niyi lati ja fun iran wa, ki a le bọ patapata.”

 

Leave a Reply