Ipo Alaafin: Awọn Ọyọmesi tun pe Gomina Makinde lẹjọ

Ọlawale Ajao, Ibadan

Lẹyin ti ile-ẹjọ ti da ẹjọ ti wọn pe ta ko gomina ipinlẹ Ọyọ, Ẹnjinnia Ṣeyi Makinde, ati igbimọ ijọba rẹ lori ọrọ oye ọba ilu Ọyọ nu, igbimọ awọn afọbaje ilu naa ti tun gbe Makinde lọ si kootu, wọn ni idajọ to da a lare lọjọsi ko tẹ awọn lọrun rara.

Lọjọ Iṣẹgun, Tusidee, ọjọ kẹrinlnlogun (16), oṣu Kẹrin, ọdun 2024 yii, l’Onidaajọ Ladiran Akintọla, ti i ṣe adajọ ile-ẹjọ gjga ipinlẹ Ọyọ to wa niluu Aawẹ, nitosi Ọyọ, da ẹjọ naa nu patapata.

Marun-un ninu awọn Ọyọmesi yii, ti wọn tun jẹ Afọbajẹ ilu Ọyọ, ni wọn pẹjọ, wọn ni ijọba ipinlẹ Ọyọ, labẹ akoso Gomina Ṣeyi Makinde, ko gbọdọ yẹ awọn lọwọ wo lori gbogbo igbesẹ ti awọn ti gbe lati gbe ọba tuntun gori itẹ gẹgẹ bii Alaafin tilu Ọyọ, nitori ọna ti awọn gbe kinni ọhun gba daa, o si wa ni ibamu pẹlu ofin ati ilana ifọbajẹ.

Nitori naa, wọn ni ki ile-ẹjọ paṣẹ fun Gomina Makinde ati kọmiṣanna feto idajọ pẹlu kọmiṣanna fọrọ oye jijẹ nipinlẹ naa lati fara mọ ẹni ti awọn fa kalẹ lati jọba, ki ijọba gbe ọpa aṣẹ fun un gẹgẹ bii Alaafin tuntun.

Wọn ni ẹni to n jẹ Ọmọọba Lukman Gbadegẹṣin ninu awọn ọmọ oye to n dupo ọba lawọn yan gẹgẹ bii Alaafin tuntun ni ọgbọnjọ (30), oṣu Kẹsan-an, ọdun 2023 yii, awọn si ti fi orukọ rẹ ransẹ si ijọba,

awọn ko si fẹ ki wọn fagi le igbesẹ ti awọn fi yan ọkunrin naa bi ko ṣe pe ki wọn tẹwọ gba a, ki wọn si ṣe eto gbogbo lati gbe e gori itẹ.

Bakan naa ni wọn rọ ile-ẹjọ lati paṣẹ fun ijọba ipinlẹ Ọyọ pe wọn ko gbọdọ fi ibinu ẹjọ ti awọn pe yii rọ awọn loye, tabi yan awọn afọbajẹ mi-in lati fi ẹlomi-in to yatọ si Ọmọọba Gbadegẹṣin ti awọn ti fa kalẹ yii jọba.

Baṣọrun ilu Ọyọ, Agba-Oye Yusuf Layinka, to jẹ olori awọn Ọyọmesi (afọbajẹ), lo lewaju awọn olupẹjọ naa.

Orukọ awọn Ọyọmesi mẹrin yooku ni Lagunna ilu Ọyọ, Agba-Oye Wakeel Oyedepo; Akinniku, Agba-Oye Amusa Yusuf; Aarẹago Baṣọrun, Oloye Wahab Oyetunji; ati Alapo tilu Ọyọ, Oloye Gbadebọ Mufutau.

Koko ohun ti wọn tori ẹ pẹjọ ni pe ki ile-ẹjọ paṣẹ fun ijọba ipinlẹ Ọyọ lati ma ṣe tun yan ọmọ oye mi-in ti yoo jẹ Alaafin mọ, nitori nigba ti awọn yan Ọmọọba Gbadegẹṣin, gbogbo ofin ati ilana pata lawọn tẹle.

Nigba to n sọrọ lori awijare awọn olupẹjọ, Onidaajọ Akintọla, sọ pe niwọn igba ti awọn afọbajẹ ko ti fi abajade ipade ti wọn fi fa Alaafin tuntun kalẹ to ijọba leti ni ibamu pẹlu ilana, a jẹ pe ohun ti wọn ṣe ọhun ku diẹ kaato, nitori naa, ẹjọ ti wọn pe ko lẹsẹ nilẹ rara.

Gẹgẹ b’ALAROYE ṣe gbọ, ko ju wakati meloo kan lọ ti ile-ẹjọ da ẹjọ ọhun nu, ti olori awọn agbejọro awọn olupẹjọ, Amofin-Agba Kunle Ṣọbaloju, ti pẹjọ kotẹmilọrun lori ọran naa.

Tẹ o ba gbagbe, l’Ọjọbọ, Tọsidee, ọjọ keji, oṣu Kọkanla, ọdun 2023, nile-ẹjọ yii ti kọ fagi le awijare awọn olupẹjọ, ti wọn si tun gbe ẹjọ mi-in dide ko too di pe ipa awọn eeyan naa pin nigba ti ile-ẹjọ da ẹjọ ọhun nu patapata.

Leave a Reply